Prev  

26. Surah Ash-Shu'arâ' سورة الشعراء

  Next  




Ayah  26:1  الأية
    +/- -/+  
بِسْم ِ اللهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ
طسم
Yoruba
 
Tọ̄ sīn mīm. (Allāhu ló mọ ohun tí Ó gbàlérò pẹ̀lú àwọn háràfí náà.)

Ayah  26:2  الأية
    +/- -/+  
تِلْكَ آيَاتُ الْكِتَابِ الْمُبِينِ
Yoruba
 
Ìwọ̀nyí ni àwọn āyah Tírà tó ń yanjú ọ̀rọ̀ ẹ̀dá.

Ayah  26:3  الأية
    +/- -/+  
لَعَلَّكَ بَاخِعٌ نَّفْسَكَ أَلَّا يَكُونُوا مُؤْمِنِينَ
Yoruba
 
Nítorí kí ni o ṣe máa para rẹ pé wọn kò jẹ́ onígbàgbọ́ òdodo.

Ayah  26:4  الأية
    +/- -/+  
إِن نَّشَأْ نُنَزِّلْ عَلَيْهِم مِّنَ السَّمَاءِ آيَةً فَظَلَّتْ أَعْنَاقُهُمْ لَهَا خَاضِعِينَ
Yoruba
 
Tí A bá fẹ́, A máa sọ àmì kan kalẹ̀ fún wọn láti sánmọ̀. Àwọn ọrùn wọn kò sì níí yé tẹríba fún un.

Ayah  26:5  الأية
    +/- -/+  
وَمَا يَأْتِيهِم مِّن ذِكْرٍ مِّنَ الرَّحْمَٰنِ مُحْدَثٍ إِلَّا كَانُوا عَنْهُ مُعْرِضِينَ
Yoruba
 
Kò sí ìrántí kan tí ó máa dé bá wọn ní titun láti ọ̀dọ̀ Àjọkẹ́-ayé àfi kí wọ́n jẹ́ olùgbúnrí kúrò níbẹ̀.

Ayah  26:6  الأية
    +/- -/+  
فَقَدْ كَذَّبُوا فَسَيَأْتِيهِمْ أَنبَاءُ مَا كَانُوا بِهِ يَسْتَهْزِئُونَ
Yoruba
 
Dájúdájú wọ́n ti pe (āyah Wa) nírọ́. Nítorí náà, àwọn ìró ohun tí wọ́n ń fi ṣe yẹ̀yẹ́ ń bọ̀ wá bá wọn.

Ayah  26:7  الأية
    +/- -/+  
أَوَلَمْ يَرَوْا إِلَى الْأَرْضِ كَمْ أَنبَتْنَا فِيهَا مِن كُلِّ زَوْجٍ كَرِيمٍ
Yoruba
 
Ṣé wọn kò rí ilẹ̀ pé mélòó mélòó nínú gbogbo oríṣiríṣi n̄ǹkan alápọ̀n-ọ́nlé tí A mú hù jáde láti inú rẹ̀?

Ayah  26:8  الأية
    +/- -/+  
إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ
Yoruba
 
Dájúdájú àmì wà nínú ìyẹn. Síbẹ̀síbẹ̀ ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ wọn kò jẹ́ onígbàgbọ́ òdodo.

Ayah  26:9  الأية
    +/- -/+  
وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ
Yoruba
 
Dájúdájú Olúwa rẹ, Òun mà ni Alágbára, Àṣàkẹ́-ọ̀run.

Ayah  26:10  الأية
    +/- -/+  
وَإِذْ نَادَىٰ رَبُّكَ مُوسَىٰ أَنِ ائْتِ الْقَوْمَ الظَّالِمِينَ
Yoruba
 
(Rántí) nígbà tí Olúwa rẹ pe (Ànábì) Mūsā pé: "Lọ bá ìjọ alábòsí,

Ayah  26:11  الأية
    +/- -/+  
قَوْمَ فِرْعَوْنَ ۚ أَلَا يَتَّقُونَ
Yoruba
 
Ìjọ Fir‘aon (kí o sì sọ̱ fún wọn) pé, ‘Ṣé wọn kò níí bẹ̀rù (Allāhu) ni.' "

Ayah  26:12  الأية
    +/- -/+  
قَالَ رَبِّ إِنِّي أَخَافُ أَن يُكَذِّبُونِ
Yoruba
 
Ó sọ pé: "Olúwa mi, dájúdájú èmi ń bẹ̀rù pé wọ́n máa pè mí ní òpùrọ́.

Ayah  26:13  الأية
    +/- -/+  
وَيَضِيقُ صَدْرِي وَلَا يَنطَلِقُ لِسَانِي فَأَرْسِلْ إِلَىٰ هَارُونَ
Yoruba
 
Ó sì máa jẹ́ ìnira fún mi (tí wọ́n bá pè mí ní òpùrọ́). Ahọ́n mi kò sì já gaaraga. Nítorí náà, ránṣẹ́ sí Hārūn.

Ayah  26:14  الأية
    +/- -/+  
وَلَهُمْ عَلَيَّ ذَنبٌ فَأَخَافُ أَن يَقْتُلُونِ
Yoruba
 
Àti pé mo ní ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́rùn lọ́dọ̀ wọn. Nítorí náà, mò ń bẹ̀rù pé wọ́n máa pa mí."

Ayah  26:15  الأية
    +/- -/+  
قَالَ كَلَّا ۖ فَاذْهَبَا بِآيَاتِنَا ۖ إِنَّا مَعَكُم مُّسْتَمِعُونَ
Yoruba
 
(Allāhu) sọ pé: "Rárá (wọn kò lè pa ọ́). Nítorí náà, kí ẹ̀yin méjèèjì mú àwọn àmì (iṣẹ́ ìyanu) Wa lọ (bá wọn). Dájúdájú Àwa ń bẹ pẹ̀lú yín; À ń gbọ́ (ọ̀rọ̀ yín).

Ayah  26:16  الأية
    +/- -/+  
فَأْتِيَا فِرْعَوْنَ فَقُولَا إِنَّا رَسُولُ رَبِّ الْعَالَمِينَ
Yoruba
 
Ẹ̀yin méjèèjì, ẹ lọ bá Fir‘aon. Kí ẹ sọ fún un pé: "Dájúdájú àwa ni Òjíṣẹ́ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.

Ayah  26:17  الأية
    +/- -/+  
أَنْ أَرْسِلْ مَعَنَا بَنِي إِسْرَائِيلَ
Yoruba
 
(À ń sọ fún ọ) pé kí o jẹ́ kí àwọn ọmọ 'Isrọ̄'īl máa bá wa lọ."

Ayah  26:18  الأية
    +/- -/+  
قَالَ أَلَمْ نُرَبِّكَ فِينَا وَلِيدًا وَلَبِثْتَ فِينَا مِنْ عُمُرِكَ سِنِينَ
Yoruba
 
(Fir‘aon) wí pé: "Ṣé kì í ṣe ní ààrin wa ni a ti tọ́ ọ ní kékeré ni, tí o sì gbé ní ọ̀dọ̀ wa fún ọdún púpọ̀ nínú ìṣẹ̀mí ayé rẹ?

Ayah  26:19  الأية
    +/- -/+  
وَفَعَلْتَ فَعْلَتَكَ الَّتِي فَعَلْتَ وَأَنتَ مِنَ الْكَافِرِينَ
Yoruba
 
O sì ṣe iṣẹ́ ọwọ́ rẹ tí o ṣe (sí wa). Ìwọ sì wà nínú àwọn aláìmoore."

Ayah  26:20  الأية
    +/- -/+  
قَالَ فَعَلْتُهَا إِذًا وَأَنَا مِنَ الضَّالِّينَ
Yoruba
 
(Ànábì Mūsā) sọ pé: "Mo ṣe é nígbà náà nígbà tí mo wà nínú àwọn aláṣìṣe (èmi kò mọ̀ọ́mọ̀ ṣe é).

Ayah  26:21  الأية
    +/- -/+  
فَفَرَرْتُ مِنكُمْ لَمَّا خِفْتُكُمْ فَوَهَبَ لِي رَبِّي حُكْمًا وَجَعَلَنِي مِنَ الْمُرْسَلِينَ
Yoruba
 
Mo sì sá fún yín nígbà tí mo bẹ̀rù yín. Lẹ́yìn náà, Allāhu ta mí lọ́rẹ ipò Ànábì. Ó sì ṣe mí ní (ọ̀kan) nínú àwọn Òjíṣẹ́.

Ayah  26:22  الأية
    +/- -/+  
وَتِلْكَ نِعْمَةٌ تَمُنُّهَا عَلَيَّ أَنْ عَبَّدتَّ بَنِي إِسْرَائِيلَ
Yoruba
 
Àti pé ìyẹn ni ìdẹ̀ra tí ò ń ṣe ìrègún rẹ̀ lé mi lórí. Pé ó sọ àwọn ọmọ 'Isrọ̄'īl di ẹrú (ńkọ́?).

Ayah  26:23  الأية
    +/- -/+  
قَالَ فِرْعَوْنُ وَمَا رَبُّ الْعَالَمِينَ
Yoruba
 
Fir‘aon wí pé: "Kí ni Olúwa gbogbo ẹ̀dá?"

Ayah  26:24  الأية
    +/- -/+  
قَالَ رَبُّ السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ وَمَا بَيْنَهُمَا ۖ إِن كُنتُم مُّوقِنِينَ
Yoruba
 
(Ànábì Mūsā) sọ pé: "(Allāhu ni) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohunkóhun tó ń bẹ láààrin àwọn méjèèjì, tí ẹ̀yin bá jẹ́ alámọ̀dájú."

Ayah  26:25  الأية
    +/- -/+  
قَالَ لِمَنْ حَوْلَهُ أَلَا تَسْتَمِعُونَ
Yoruba
 
(Fir‘aon) wí fún àwọn tó wà ní àyíká rẹ̀ pé: "Ṣé ẹ ẹ̀ gbọ́ ọ̀rọ̀ (tó ń sọ ni)?"

Ayah  26:26  الأية
    +/- -/+  
قَالَ رَبُّكُمْ وَرَبُّ آبَائِكُمُ الْأَوَّلِينَ
Yoruba
 
(Ànábì Mūsā) sọ pé: "(Allāhu ni) Olúwa yín àti Olúwa àwọn bàbá yín, àwọn ẹni àkọ́kọ́."

Ayah  26:27  الأية
    +/- -/+  
قَالَ إِنَّ رَسُولَكُمُ الَّذِي أُرْسِلَ إِلَيْكُمْ لَمَجْنُونٌ
Yoruba
 
(Fir‘aon) wí pé: "Dájúdájú Òjíṣẹ́ yín èyí tí wọ́n rán si yín, wèrè mà ni."

Ayah  26:28  الأية
    +/- -/+  
قَالَ رَبُّ الْمَشْرِقِ وَالْمَغْرِبِ وَمَا بَيْنَهُمَا ۖ إِن كُنتُمْ تَعْقِلُونَ
Yoruba
 
(Ànábì Mūsā) sọ pé: "(Allāhu ni) Olúwa ibùyọ òòrùn, ibùwọ̀ òòrùn àti ohunkóhun tó ń bẹ láààrin àwọn méjèèjì, tí ẹ bá máa ń ṣe làákàyè."

Ayah  26:29  الأية
    +/- -/+  
قَالَ لَئِنِ اتَّخَذْتَ إِلَٰهًا غَيْرِي لَأَجْعَلَنَّكَ مِنَ الْمَسْجُونِينَ
Yoruba
 
(Fir‘aon) wí pé: "Dájúdájú tí o bá fi lè jọ́sìn fún ọlọ́hun kan yàtọ̀ sí mi, dájúdájú mo máa sọ ọ́ di ara àwọn ẹlẹ́wọ̀n."

Ayah  26:30  الأية
    +/- -/+  
قَالَ أَوَلَوْ جِئْتُكَ بِشَيْءٍ مُّبِينٍ
Yoruba
 
(Ànábì Mūsā) sọ pé: "Tí ó bá jẹ́ pé mo mú kiní kan tó yanjú wá fún ọ ńkọ́?"

Ayah  26:31  الأية
    +/- -/+  
قَالَ فَأْتِ بِهِ إِن كُنتَ مِنَ الصَّادِقِينَ
Yoruba
 
(Fir‘aon) wí pé: "Mú un wá nígbà náà tí ìwọ bá wà nínú àwọn olódodo."

Ayah  26:32  الأية
    +/- -/+  
فَأَلْقَىٰ عَصَاهُ فَإِذَا هِيَ ثُعْبَانٌ مُّبِينٌ
Yoruba
 
Nítorí náà, ó ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀, ó sì di ejò pọ́nńbélé.

Ayah  26:33  الأية
    +/- -/+  
وَنَزَعَ يَدَهُ فَإِذَا هِيَ بَيْضَاءُ لِلنَّاظِرِينَ
Yoruba
 
Ó tún fa ọwọ́ rẹ̀ yọ síta, ó sì di funfun fún àwọn olùwòran.

Ayah  26:34  الأية
    +/- -/+  
قَالَ لِلْمَلَإِ حَوْلَهُ إِنَّ هَٰذَا لَسَاحِرٌ عَلِيمٌ
Yoruba
 
(Fir‘aon) wí fún àwọn ìjòyè tí wọ́n wà ní àyíká rẹ̀ pé: "Dájúdájú èyí ni onímọ̀ nípa idán pípa.

Ayah  26:35  الأية
    +/- -/+  
يُرِيدُ أَن يُخْرِجَكُم مِّنْ أَرْضِكُم بِسِحْرِهِ فَمَاذَا تَأْمُرُونَ
Yoruba
 
Ó fẹ́ ko yín kúrò lórí ilẹ̀ yín ni. Kí ni ohun tí ẹ máa mú wá ní ìmọ̀ràn?"

Ayah  26:36  الأية
    +/- -/+  
قَالُوا أَرْجِهْ وَأَخَاهُ وَابْعَثْ فِي الْمَدَائِنِ حَاشِرِينَ
Yoruba
 
Wọ́n wí pé: "Dá òun àti arákùnrin rẹ̀ dúró ná, kí o sì rán àwọn akónijọ sí àwọn ìlú

Ayah  26:37  الأية
    +/- -/+  
يَأْتُوكَ بِكُلِّ سَحَّارٍ عَلِيمٍ
Yoruba
 
(pé) kí gbogbo onímọ̀ nípa idán pípa wá bá ọ."

Ayah  26:38  الأية
    +/- -/+  
فَجُمِعَ السَّحَرَةُ لِمِيقَاتِ يَوْمٍ مَّعْلُومٍ
Yoruba
 
Wọ́n sì kó àwọn òpìdán jọ ní àsìkò tí wọ́n fi àdéhùn sí ní ọjọ́ tí (gbogbo ìlú) ti mọ̀.

Ayah  26:39  الأية
    +/- -/+  
وَقِيلَ لِلنَّاسِ هَلْ أَنتُم مُّجْتَمِعُونَ
Yoruba
 
Wọ́n sì wí fún àwọn ènìyàn pé: "Ṣé ẹ̀yin máa kó jọ (síbẹ̀) bí?

Ayah  26:40  الأية
    +/- -/+  
لَعَلَّنَا نَتَّبِعُ السَّحَرَةَ إِن كَانُوا هُمُ الْغَالِبِينَ
Yoruba
 
Nítorí kí á lè tẹ̀lé àwọn òpìdán tí ó bá jẹ́ pé àwọn ni olùborí."

Ayah  26:41  الأية
    +/- -/+  
فَلَمَّا جَاءَ السَّحَرَةُ قَالُوا لِفِرْعَوْنَ أَئِنَّ لَنَا لَأَجْرًا إِن كُنَّا نَحْنُ الْغَالِبِينَ
Yoruba
 
Nígbà tí àwọn òpìdán dé, wọ́n wí fún Fir‘aon pé: "Ǹjẹ́ owó-ọ̀yà kan wà fún wa, tí ó bá jẹ́ pé àwa gan-an la jẹ́ olùborí?"

Ayah  26:42  الأية
    +/- -/+  
قَالَ نَعَمْ وَإِنَّكُمْ إِذًا لَّمِنَ الْمُقَرَّبِينَ
Yoruba
 
(Fir‘aon) wí pé: "Bẹ́ẹ̀ ni, dájúdájú nígbà náà ẹ máa wà nínú àwọn alásùn-únmọ́ (mi)."

Ayah  26:43  الأية
    +/- -/+  
قَالَ لَهُم مُّوسَىٰ أَلْقُوا مَا أَنتُم مُّلْقُونَ
Yoruba
 
(Ànábì) Mūsā sọ fún wọn pé: "Ẹ ju ohun tí ẹ fẹ́ jù sílẹ̀."

Ayah  26:44  الأية
    +/- -/+  
فَأَلْقَوْا حِبَالَهُمْ وَعِصِيَّهُمْ وَقَالُوا بِعِزَّةِ فِرْعَوْنَ إِنَّا لَنَحْنُ الْغَالِبُونَ
Yoruba
 
Wọ́n sì ju àwọn okùn wọn àti ọ̀pá wọn sílẹ̀. Wọ́n wí pé: "Pẹ̀lú ògo Fir‘aon, dájúdájú àwa, àwa ni olùborí."

Ayah  26:45  الأية
    +/- -/+  
فَأَلْقَىٰ مُوسَىٰ عَصَاهُ فَإِذَا هِيَ تَلْقَفُ مَا يَأْفِكُونَ
Yoruba
 
Nígbà náà, (Ànábì) Mūsā ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀. Ó sì ń gbé ohun tí wọ́n pa nírọ́ kalẹ̀ mì kálókáló.

Ayah  26:46  الأية
    +/- -/+  
فَأُلْقِيَ السَّحَرَةُ سَاجِدِينَ
Yoruba
 
Nítorí náà, iṣẹ́ ìyanu (Ànábì Mūsā) mú àwọn òpìdán wó lulẹ̀, tí wọ́n forí kanlẹ̀ (fún Allāhu).

Ayah  26:47  الأية
    +/- -/+  
قَالُوا آمَنَّا بِرَبِّ الْعَالَمِينَ
Yoruba
 
Wọ́n sọ pé: "A gbàgbọ́ nínú Olúwa gbogbo ẹ̀dá,

Ayah  26:48  الأية
    +/- -/+  

Ayah  26:49  الأية
    +/- -/+  
قَالَ آمَنتُمْ لَهُ قَبْلَ أَنْ آذَنَ لَكُمْ ۖ إِنَّهُ لَكَبِيرُكُمُ الَّذِي عَلَّمَكُمُ السِّحْرَ فَلَسَوْفَ تَعْلَمُونَ ۚ لَأُقَطِّعَنَّ أَيْدِيَكُمْ وَأَرْجُلَكُم مِّنْ خِلَافٍ وَلَأُصَلِّبَنَّكُمْ أَجْمَعِينَ
Yoruba
 
Fir‘aon wí pé: "Ẹ gbà Á gbọ́ ṣíwájú kí n̄g tó yọ̀ǹda fún yín! Dájúdájú òun ni àgbà yín tí ó kọ yín ní idán pípa. Láìpẹ́ ẹ̀ ń bọ̀ wá mọ̀. Dájúdájú mo máa gé ọwọ́ yín àti ẹsẹ̀ yín ní ìpasípayọ. Lẹ́yìn náà, dájúdájú mo máa kan gbogbo yín mọ́gi."

Ayah  26:50  الأية
    +/- -/+  
قَالُوا لَا ضَيْرَ ۖ إِنَّا إِلَىٰ رَبِّنَا مُنقَلِبُونَ
Yoruba
 
(Àwọn òpìdán) sọ pé: "Kò sí ìnira fún wa! Dájúdájú àwa yó sì fàbọ̀ sí ọ̀dọ̀ Olúwa wa.

Ayah  26:51  الأية
    +/- -/+  
إِنَّا نَطْمَعُ أَن يَغْفِرَ لَنَا رَبُّنَا خَطَايَانَا أَن كُنَّا أَوَّلَ الْمُؤْمِنِينَ
Yoruba
 
Dájúdájú àwa n retí pé Olúwa wa yóò ṣe àforíjìn àwọn àṣìṣe wa fún wa nítorí pé àwa jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ (tí ó jẹ́) onígbàgbọ́ òdodo."

Ayah  26:52  الأية
    +/- -/+  
وَأَوْحَيْنَا إِلَىٰ مُوسَىٰ أَنْ أَسْرِ بِعِبَادِي إِنَّكُم مُّتَّبَعُونَ
Yoruba
 
A fi ìmísí ránṣẹ́ sí (Ànábì) Mūsā pé: "Mú àwọn ẹrúsìn Mi rìn ní òru (nítorí pé), dájúdájú wọn yóò lépa yín."

Ayah  26:53  الأية
    +/- -/+  
فَأَرْسَلَ فِرْعَوْنُ فِي الْمَدَائِنِ حَاشِرِينَ
Yoruba
 
Fir‘aon sì rán àwọn akónijọ sínú àwọn ìlú (láti sọ pé):

Ayah  26:54  الأية
    +/- -/+  
إِنَّ هَٰؤُلَاءِ لَشِرْذِمَةٌ قَلِيلُونَ
Yoruba
 
"Dájúdájú àwọn (ọmọ 'Isrọ̄'īl) wọ̀nyí, ìjọ péréte díẹ̀ ni wọ́n.

Ayah  26:55  الأية
    +/- -/+  
وَإِنَّهُمْ لَنَا لَغَائِظُونَ
Yoruba
 
Àti pé dájúdájú wọ́n ti ṣe ohun tó ń bí wa nínú.

Ayah  26:56  الأية
    +/- -/+  
وَإِنَّا لَجَمِيعٌ حَاذِرُونَ
Yoruba
 
Dájúdájú gbogbo wa ni kí á sì wà tìfura-tìfura."

Ayah  26:57  الأية
    +/- -/+  
فَأَخْرَجْنَاهُم مِّن جَنَّاتٍ وَعُيُونٍ
Yoruba
 
Nítorí náà, A mú (ìjọ Fir‘aon) jáde kúrò nínú àwọn ọgbà oko àti ìṣẹ́lẹ̀rú omi,

Ayah  26:58  الأية
    +/- -/+  
وَكُنُوزٍ وَمَقَامٍ كَرِيمٍ
Yoruba
 
Àti àwọn ilé ọrọ̀ àti ibùjókòó àpọ́nlé.

Ayah  26:59  الأية
    +/- -/+  
كَذَٰلِكَ وَأَوْرَثْنَاهَا بَنِي إِسْرَائِيلَ
Yoruba
 
Báyẹn (lọ̀rọ̀ rí). A sì jogún rẹ̀ fún àwọn ọmọ 'Isrọ̄'īl.

Ayah  26:60  الأية
    +/- -/+  
فَأَتْبَعُوهُم مُّشْرِقِينَ
Yoruba
 
Wọ́n sì lépa wọn ní àsìkò tí òòrùn yọ.

Ayah  26:61  الأية
    +/- -/+  
فَلَمَّا تَرَاءَى الْجَمْعَانِ قَالَ أَصْحَابُ مُوسَىٰ إِنَّا لَمُدْرَكُونَ
Yoruba
 
Nígbà tí ìjọ méjèèjì ríra wọn, àwọn ìjọ (Ànábì) Mūsā sọ pé: "Dájúdájú wọn yóò lé wa bá."

Ayah  26:62  الأية
    +/- -/+  
قَالَ كَلَّا ۖ إِنَّ مَعِيَ رَبِّي سَيَهْدِينِ
Yoruba
 
(Ànábì) Mūsā sọ pé: "Rárá, dájúdájú Olúwa mi ń bẹ pẹ̀lú mi. Ó sì máa fi ọ̀nà mọ̀ mí."

Ayah  26:63  الأية
    +/- -/+  
فَأَوْحَيْنَا إِلَىٰ مُوسَىٰ أَنِ اضْرِب بِّعَصَاكَ الْبَحْرَ ۖ فَانفَلَقَ فَكَانَ كُلُّ فِرْقٍ كَالطَّوْدِ الْعَظِيمِ
Yoruba
 
A sì fi ìmísí ránṣẹ́ sí (Ànábì) Mūsā pé: "Fi ọ̀pá rẹ na agbami òkun." (Ó fi nà án). Ó sì pín (sí ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀). Ìpín kọ̀ọ̀kan sì dà bí àpáta ńlá.

Ayah  26:64  الأية
    +/- -/+  
وَأَزْلَفْنَا ثَمَّ الْآخَرِينَ
Yoruba
 
A sì mú ìjọ kejì (ìyẹn, ìjọ Fir‘aon) súnmọ́ ibẹ̀ yẹn.

Ayah  26:65  الأية
    +/- -/+  
وَأَنجَيْنَا مُوسَىٰ وَمَن مَّعَهُ أَجْمَعِينَ
Yoruba
 
A gba (Ànábì) Mūsā àti gbogbo àwọn tó ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ là pátápátá.

Ayah  26:66  الأية
    +/- -/+  
ثُمَّ أَغْرَقْنَا الْآخَرِينَ
Yoruba
 
Lẹ́yìn náà, A tẹ ìjọ kejì rì (sínú agbami).

Ayah  26:67  الأية
    +/- -/+  
إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ
Yoruba
 
Dájúdájú àmì wà nínú ìyẹn. Síbẹ̀síbẹ̀ ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ wọn kò jẹ́ onígbàgbọ́ òdodo.

Ayah  26:68  الأية
    +/- -/+  
وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ
Yoruba
 
Dájúdájú Olúwa rẹ, Òun mà ni Alágbára, Àṣàkẹ́-ọ̀run.

Ayah  26:69  الأية
    +/- -/+  
وَاتْلُ عَلَيْهِمْ نَبَأَ إِبْرَاهِيمَ
Yoruba
 
Ka ìròyìn (Ànábì) 'Ibrọ̄hīm fún wọn.

Ayah  26:70  الأية
    +/- -/+  
إِذْ قَالَ لِأَبِيهِ وَقَوْمِهِ مَا تَعْبُدُونَ
Yoruba
 
Nígbà tí ó sọ fún bàbá rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: "Kí ni n̄ǹkan tí ẹ̀ ń jọ́sìn fún ná?"

Ayah  26:71  الأية
    +/- -/+  
قَالُوا نَعْبُدُ أَصْنَامًا فَنَظَلُّ لَهَا عَاكِفِينَ
Yoruba
 
Wọ́n wí pé: "À ń jọ́sìn fún àwọn ère òrìṣà kan ni. A ò sì níí yé takú tì wọ́n lọ́rùn."

Ayah  26:72  الأية
    +/- -/+  
قَالَ هَلْ يَسْمَعُونَكُمْ إِذْ تَدْعُونَ
Yoruba
 
(Ànábì 'Ibrọ̄hīm) sọ pé: "Ǹjẹ́ wọ́n ń gbọ́ ọ̀rọ̀ yín nígbà tí ẹ bá ń pè wọ́n?

Ayah  26:73  الأية
    +/- -/+  
أَوْ يَنفَعُونَكُمْ أَوْ يَضُرُّونَ
Yoruba
 
Tàbí (ṣé) wọ́n lè ṣe yín ní àǹfààní tàbí wọ́n lè fi ìnira kàn yín?"

Ayah  26:74  الأية
    +/- -/+  
قَالُوا بَلْ وَجَدْنَا آبَاءَنَا كَذَٰلِكَ يَفْعَلُونَ
Yoruba
 
Wọ́n wí pé: "Rárá o! A bá àwọn bàbá wa tí wọ́n ń ṣe bẹ́ẹ̀ ni"

Ayah  26:75  الأية
    +/- -/+  
قَالَ أَفَرَأَيْتُم مَّا كُنتُمْ تَعْبُدُونَ
Yoruba
 
(Ànábì 'Ibrọ̄hīm) sọ pé: " Ẹ sọ fún mi, kí ni n̄ǹkan tí ẹ̀ ń jọ́sìn fún,

Ayah  26:76  الأية
    +/- -/+  
أَنتُمْ وَآبَاؤُكُمُ الْأَقْدَمُونَ
Yoruba
 
ẹ̀yin àti àwọn bàbá yín àwọn ẹni ìṣáájú?

Ayah  26:77  الأية
    +/- -/+  
فَإِنَّهُمْ عَدُوٌّ لِّي إِلَّا رَبَّ الْعَالَمِينَ
Yoruba
 
Dájúdájú àwọn ni ọ̀tá fún mi àyàfi Olúwa gbogbo ẹ̀dá.

Ayah  26:78  الأية
    +/- -/+  
الَّذِي خَلَقَنِي فَهُوَ يَهْدِينِ
Yoruba
 
(Òun ni) Ẹni tí Ó ṣẹ̀dá mi. Nítorí náà, Ó máa fi ọ̀nà mọ̀ mí;

Ayah  26:79  الأية
    +/- -/+  
وَالَّذِي هُوَ يُطْعِمُنِي وَيَسْقِينِ
Yoruba
 
Ẹni tó ń fún mi ní jíjẹ, tó ń fún mi ní mímu;

Ayah  26:80  الأية
    +/- -/+  
وَإِذَا مَرِضْتُ فَهُوَ يَشْفِينِ
Yoruba
 
Àti pé nígbà tí ara mi kò bá yá, Òun l'Ó ń wò mí sàn;

Ayah  26:81  الأية
    +/- -/+  
وَالَّذِي يُمِيتُنِي ثُمَّ يُحْيِينِ
Yoruba
 
Ẹni tí Ó máa pa mí, lẹ́yìn náà, Ó máa sọ mí di alààyè;

Ayah  26:82  الأية
    +/- -/+  
وَالَّذِي أَطْمَعُ أَن يَغْفِرَ لِي خَطِيئَتِي يَوْمَ الدِّينِ
Yoruba
 
Ẹni tí mo ní ìrètí sí pé Ó máa forí àwọn àṣìṣe mi jìn mí ní Ọjọ́ Ẹ̀san.